Al-Harith bin Hammam narrated, saying: I sensed hardness in my heart
Hárìsù ọmọ Hammám sọ̀rọ̀ pé: Mo rí líle ọkàn nínú àyà mi
When I arrived at Sawah
Nígbà tí mo dé ìlú Sáwà
So I followed the traditional wisdom of treating it by visiting the graves
Nítorí náà, mo tẹ̀lé ọgbọ́n àtọwọ́dọ́wọ́ láti wò ó sàn nípa lílọ́ sí ibojì
When I reached the dwelling place of the dead and the repository of remains
Nígbà tí mo dé ibùgbé àwọn òkú àti ibi ìpamọ́ egungun
I saw a gathering at a grave being dug and a deceased being buried
Mo rí ọpọ ènìyàn ní ibi tí wọ́n tí ń gbẹ́ ibojì kan tí wọ́n sì ńsin òkú kan
So I joined them, contemplating the final fate and remembering those of my family who had passed
Mo sì dàpọ̀ mọ́ wọn, mo ńrònú nípa ìgbẹ̀hìn ayé, mo ńrántí àwọn ará ilé mi tó ti kú
When they laid the deceased in the grave and the time for 'if only' had passed
Nígbà tí wọ́n ti tẹ́ òkú sí ibojì tí àkókò 'ìbáà ṣe' sì ti kọjá
An elder appeared from a hill, leaning on a staff, having wrapped his face with his cloak and disguised his persona through his cunning
Àgbàlagbà kan yọjú láti orí òkè, ó fi ọ̀pá tì ara, ó si fi aṣọ bo ojú rẹ̀, ó sì pa ara rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú ọgbọ́ń ète rẹ
He said: For the end like this, let the workers work
Ó sọ pé: Fún irú ìgbẹ̀yìn yí ni kí àwọn oníṣẹ́ ṣiṣẹ́
So remember, O you who are heedless
Nítorí náà, ẹ rántí, ẹ̀yin tí ẹ ń ṣe àìmọ̀kan